ORIN 31
Bá Ọlọ́run Rìn!
(Míkà 6:8)
-
1. Fìrẹ̀lẹ̀ bá Ọlọ́run rìn;
Sún mọ́ ọn, kó o sì gbára lé e.
Jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà,
Ó sì máa fún ẹ lókun.
Tó o bá rọ̀ mọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,
Kò ní jẹ́ kó o ṣìnà.
Tó o bá ń ṣègbọràn s’Ọ́lọ́run,
Á tọ́ ẹ sọ́nà ìyè.
-
2. Fìwà mímọ́ b’Ọ́lọ́run rìn;
Fọkàn sí ohun mímọ́.
Kò sí bí àdánwò ṣe fẹ́ le tó,
Yóò jẹ́ kó o lè fara dàá.
Ohunkóhun tó yẹ fún ìyìn,
Tó sì jẹ́ òtítọ́
Ni kó o máa rò nígbà gbogbo;
Jáà yóò sì wà pẹ̀lú rẹ.
-
3. Fi ayọ̀ bá Ọlọ́run rìn;
Máa yọ̀ pó o jẹ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Dúpẹ́ fún gbogbo ẹ̀bùn tó fún ọ
Àti bó ṣe ń bù kún ọ.
Bóo ṣe ń bá Ọlọ́run tòótọ́ rìn,
Máa fayọ̀ kọrin sí i.
Èyí yóò jẹ́ káráyé mọ̀
Pé Jèhófà lò ń bá rìn.
(Tún wo Jẹ́n. 5:24; 6:9; Fílí. 4:8; 1 Tím. 6:6-8.)