ORIN 68
Máa Fún Irúgbìn Ìjọba Náà
-
1. Ọ̀gá wa ń pè ọ́ pé kóo máa bọ̀,
Kó o wá ṣe nínú iṣẹ́ rẹ̀.
Fọkàn balẹ̀, yóò tọ́ ẹ sọ́nà,
Ó sì tún máa dá ẹ lẹ́kọ̀ọ́.
Inú ọkàn àwọn onírẹ̀lẹ̀
Nirúgbìn òótọ́ ti máa ń hù.
Torí náà, rí i pé o sa gbogbo ‘pá rẹ
Kó o lè ṣiṣẹ́ tá a yàn fún ọ yìí.
-
2. Tíṣẹ́ rẹ bá máa sèso rere,
Nígbà míì, ọwọ́ rẹ ló wà.
Fìfẹ́ kọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ rẹ
Kí wọ́n lè nífẹ̀ẹ́ òtítọ́.
Kọ́ wọn bí wọ́n ṣe máa kojú ‘ṣòro
Àt’àdánwò tó bá yọjú.
Inú rẹ máa dùn tó o bá rí bí wọ́n ṣe
Ń fi òótọ́ tí wọ́n ń kọ́ yìí sílò.
(Tún wo Mát. 13:19-23; 22:37.)