Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Ṣé Ẹ Gbà Pé Ẹ̀sìn Yín Nìkan Lẹ̀sìn Tòótọ́?

Ṣé Ẹ Gbà Pé Ẹ̀sìn Yín Nìkan Lẹ̀sìn Tòótọ́?

 Àwọn tí wọ́n bá fi ọwọ́ pàtàkì mú ẹ̀sìn ní láti gbà pé Ọlọ́run àti Jésù fara mọ́ ẹ̀sìn wọn. Ká ní wọn kò gbà bẹ́ẹ̀ ni, ṣé wọ́n á máa ṣe é?

 Jésù Kristi kò fara mọ́ èrò àwọn kan pé ọ̀pọ̀ ẹ̀sìn tàbí ọ̀pọ̀ ọ̀nà ló wà, pé gbogbo wọn ló máa ṣamọ̀nà sí ìgbàlà. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó sọ pé: “Tóóró ni ẹnubodè náà, híhá sì ni ojú ọ̀nà tí ó lọ sínú ìyè, díẹ̀ sì ni àwọn tí ń rí i.” (Mátíù 7:14) Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà gbà pé wọ́n ti rí ọ̀nà yẹn. Bí kì í bá ṣe bẹ́ẹ̀ ni, wọn ì bá ti wá ẹ̀sìn míì.