Jóòbù 17:1-16

  • Jóòbù ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ (1-16)

    • “Àwọn tó ń fini ṣe yẹ̀yẹ́ yí mi ká” (2)

    • “Ó ti sọ mí di ẹni ẹ̀gàn” (6)

    • “Isà Òkú máa di ilé mi” (13)

17  “Ìbànújẹ́ ti bá ẹ̀mí mi, àwọn ọjọ́ mi ti dópin;Itẹ́ òkú ń retí mi.+   Àwọn tó ń fini ṣe yẹ̀yẹ́ yí mi ká,+Àfi kí ojú mi máa wo* ìwà ọ̀tẹ̀ wọn.   Jọ̀ọ́, gba ohun tí mo fi ṣe ìdúró, kí o sì tọ́jú rẹ̀ sọ́dọ̀ rẹ. Ta ló tún máa bọ̀ mí lọ́wọ́, tó sì máa dúró fún mi?+   Torí o ò jẹ́ kí ọkàn wọn ní òye;+Ìdí nìyẹn tí o kò fi gbé wọn ga.   Ó lè fẹ́ kí òun àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ pín in,Síbẹ̀, ojú àwọn ọmọ rẹ̀ ń ṣú.   Ó ti sọ mí di ẹni ẹ̀gàn* láàárín àwọn èèyàn,+Tí mo fi di ẹni tí wọ́n ń tutọ́ sí lójú.+   Ìrora ti sọ ojú mi di bàìbàì,+Òjìji sì ni gbogbo apá àti ẹsẹ̀ mi.   Àwọn olóòótọ́ ń wo èyí tìyanutìyanu,Ọkàn aláìṣẹ̀ ò sì balẹ̀ torí ẹni tí kò mọ Ọlọ́run.*   Olódodo kò fi ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ rárá,+Ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ mọ́ sì ń lágbára sí i.+ 10  Àmọ́ gbogbo yín tún lè wá máa ro ẹjọ́ yín,Torí mi ò rí ọlọ́gbọ́n kankan nínú yín.+ 11  Àwọn ọjọ́ mi ti dópin;+Àwọn ohun tí mo fẹ́ ṣe, àwọn ohun tí ọkàn mi fẹ́, ti já sí asán.+ 12  Wọ́n ń sọ òru di ọ̀sán,Wọ́n ń sọ pé, ‘Ó ní láti jẹ́ pé ìmọ́lẹ̀ wà nítòsí torí òkùnkùn ṣú.’ 13  Tí mo bá dúró, Isà Òkú* máa di ilé mi;+Màá tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn.+ 14  Màá ké pe ihò*+ pé, ‘Ìwọ ni bàbá mi!’ Àti ìdin pé, ‘Ìyá mi àti arábìnrin mi!’ 15  Ibo wá ni ìrètí mi+ wà? Ta ló lè bá mi rí ìrètí? 16  Ó* máa sọ̀ kalẹ̀ lọ sí àwọn ẹnubodè Isà Òkú* tí wọ́n tì paTí gbogbo wa bá jọ sọ̀ kalẹ̀ lọ sínú iyẹ̀pẹ̀.”+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “kí n tẹjú mọ́.”
Ní Héb., “àfipòwe.”
Tàbí “apẹ̀yìndà.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “sàréè.”
Ìyẹn, ìrètí mi.
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.