Nọ́ńbà 11:1-35

  • Iná bọ́ látọ̀dọ̀ Ọlọ́run torí wọ́n ń ráhùn (1-3)

  • Wọ́n ń sunkún torí wọ́n fẹ́ jẹ ẹran (4-9)

  • Mósè wò ó pé òun ò kúnjú ìwọ̀n (10-15)

  • Jèhófà fi ẹ̀mí sára 70 àgbààgbà (16-25)

  • Ẹ́lídádì àti Médádì; Jóṣúà ń jowú torí Mósè (26-30)

  • Àwọn ẹyẹ àparò wá; Ọlọ́run fìyà jẹ wọ́n torí ìwọra wọn (31-35)

11  Àwọn èèyàn náà bá bẹ̀rẹ̀ sí í ráhùn gidigidi níwájú Jèhófà. Nígbà tí Jèhófà gbọ́, inú bí i gan-an, iná sì wá látọ̀dọ̀ Jèhófà, ó jó àwọn kan tó wà ní ìkángun ibùdó náà run.  Nígbà tí àwọn èèyàn náà bẹ̀rẹ̀ sí í ké pe Mósè, ó rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí Jèhófà,+ iná náà sì kú.  Wọ́n wá pe orúkọ ibẹ̀ ní Tábérà,* torí pé iná látọ̀dọ̀ Jèhófà jó wọn.+  Onírúurú èèyàn*+ tó wà láàárín wọn bá bẹ̀rẹ̀ sí í fi ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn+ wọn hàn, àwọn ọmọ Ísírẹ́lì náà tún wá ń sunkún, wọ́n sì ń sọ pé: “Ta ló máa fún wa ní ẹran jẹ?+  A ò jẹ́ gbàgbé ẹja tí a máa ń jẹ lọ́fẹ̀ẹ́ nílẹ̀ Íjíbítì àti kùkúńbà,* bàrà olómi, ewébẹ̀ líìkì, àlùbọ́sà àti ááyù!+  Àmọ́ ní báyìí, a* ti ń kú lọ. A ò rí nǹkan míì jẹ yàtọ̀ sí mánà+ yìí.”  Ó ṣẹlẹ̀ pé mánà+ náà dà bí irúgbìn kọriáńdà,+ ó sì rí bíi gọ́ọ̀mù bídẹ́líọ́mù.  Àwọn èèyàn náà máa ń lọ káàkiri láti kó o, wọ́n á sì fi ọlọ lọ̀ ọ́ tàbí kí wọ́n gún un nínú odó. Wọ́n á wá sè é nínú ìkòkò tàbí kí wọ́n fi ṣe búrẹ́dì ribiti,+ bí àkàrà dídùn tí wọ́n fi òróró sí ló rí lẹ́nu.  Tí ìrì bá sẹ̀ sí ibùdó náà ní òru, mánà náà máa ń já bọ́ sórí rẹ̀.+ 10  Mósè gbọ́ bí àwọn èèyàn náà ṣe ń sunkún, ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, kálukú wà lẹ́nu ọ̀nà àgọ́ rẹ̀. Inú bí Jèhófà gan-an,+ inú Mósè náà ò sì dùn rárá. 11  Mósè wá sọ fún Jèhófà pé: “Kí ló dé tí o fìyà jẹ ìránṣẹ́ rẹ? Kí ló dé tí o kò ṣojúure sí mi, tí o sì di ẹrù gbogbo àwọn èèyàn yìí lé mi lórí?+ 12  Ṣé èmi ni mo lóyún gbogbo àwọn èèyàn yìí ni? Àbí èmi ni mo bí wọn, tí o fi ń sọ fún mi pé, ‘Gbé wọn sí àyà rẹ bí olùtọ́jú* ṣe máa ń gbé ọmọ tó ṣì ń mu ọmú’ lọ sí ilẹ̀ tí o búra pé o máa fún àwọn baba ńlá+ wọn? 13  Ibo ni kí n ti rí ẹran tí màá fún gbogbo àwọn èèyàn yìí? Torí wọ́n ń sunkún sí mi lọ́rùn, wọ́n ń sọ pé, ‘Fún wa ní ẹran jẹ!’ 14  Èmi nìkan ò lè gbé ẹrù gbogbo àwọn èèyàn yìí, ó ti wúwo jù fún mi.+ 15  Tó bá jẹ́ ohun tí o fẹ́ ṣe fún mi nìyí, jọ̀ọ́ kúkú pa mí báyìí.+ Tí mo bá rí ojúure rẹ, má ṣe jẹ́ kí ojú mi tún rí ibi mọ́.” 16  Jèhófà wá dá Mósè lóhùn pé: “Kó àádọ́rin (70) ọkùnrin jọ fún mi nínú àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì, àwọn tí o mọ̀ pé wọ́n jẹ́* àgbààgbà àti olórí láàárín àwọn èèyàn náà,+ kí o mú wọn lọ sí àgọ́ ìpàdé, kí wọ́n sì dúró níbẹ̀ pẹ̀lú rẹ. 17  Èmi yóò sọ̀ kalẹ̀+ wá bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀,+ mo máa mú lára ẹ̀mí+ tó wà lára rẹ, màá sì fi sára wọn, wọ́n á sì máa ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ru ẹrù àwọn èèyàn náà, kí o má bàa dá ru ẹrù náà.+ 18  Kí o sọ fún àwọn èèyàn náà pé, ‘Ẹ sọ ara yín di mímọ́ de ọ̀la,+ ó dájú pé ẹ máa jẹ ẹran, torí Jèhófà ti gbọ́+ ẹkún tí ẹ̀ ń sun pé: “Ta ló máa fún wa ní ẹran jẹ? Nǹkan sàn ju báyìí lọ fún wa ní Íjíbítì.”+ Ó dájú pé Jèhófà máa fún yín ní ẹran, ẹ ó sì jẹ ẹ́.+ 19  Ẹ máa jẹ ẹ́, kì í ṣe ọjọ́ kan tàbí méjì lẹ máa fi jẹ ẹ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ọjọ́ márùn-ún tàbí mẹ́wàá tàbí ogún (20) ọjọ́ lẹ máa fi jẹ ẹ́, 20  àmọ́ oṣù kan gbáko ni, títí á fi jáde ní ihò imú yín, tó sì máa kó yín nírìíra,+ torí pé ẹ ti kọ Jèhófà, ẹni tó wà ní àárín yín, ẹ sì wá ń sunkún níwájú rẹ̀ pé: “Kí ló dé tí a kúrò ní Íjíbítì?”’”+ 21  Mósè wá sọ pé: “Ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ (600,000) ọkùnrin*+ la jọ wà níbí, síbẹ̀ ìwọ fúnra rẹ sọ pé, ‘Èmi yóò fún wọn ní ẹran, wọ́n á sì jẹ ẹ́ ni àjẹyó fún oṣù kan gbáko’! 22  Tí wọ́n bá pa gbogbo agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran, ṣé ó lè tó wọn? Tí wọ́n bá sì mú gbogbo ẹja inú òkun, ṣé ó máa tó wọn?” 23  Ni Jèhófà bá sọ fún Mósè pé: “Ṣé ọwọ́ Jèhófà kúrú+ ni? Ó máa ṣojú rẹ báyìí, bóyá ohun tí mo sọ máa ṣẹlẹ̀ sí ọ tàbí kò ní ṣẹlẹ̀.” 24  Mósè wá jáde lọ sọ ọ̀rọ̀ Jèhófà fún àwọn èèyàn náà. Ó sì kó àádọ́rin (70) ọkùnrin jọ lára àwọn àgbààgbà nínú àwọn èèyàn náà, ó sì mú wọn dúró yí àgọ́+ ká. 25  Jèhófà bá sọ̀ kalẹ̀ nínú ìkùukùu,*+ ó bá a+ sọ̀rọ̀, ó sì mú díẹ̀ lára ẹ̀mí+ tó wà lára rẹ̀, ó fi sára àwọn àádọ́rin (70) àgbààgbà náà lọ́kọ̀ọ̀kan. Gbàrà tí ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe bíi wòlíì,*+ àmọ́ wọn ò tún ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́. 26  Méjì lára àwọn ọkùnrin náà ṣì wà nínú ibùdó. Orúkọ wọn ni Ẹ́lídádì àti Médádì. Ẹ̀mí náà bà lé wọn torí wọ́n wà lára àwọn tí wọ́n kọ orúkọ wọn sílẹ̀, àmọ́ wọn ò lọ sí àgọ́. Wọ́n wá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe bíi wòlíì nínú ibùdó. 27  Ọ̀dọ́kùnrin kan wá sáré lọ sọ fún Mósè pé: “Ẹ́lídádì àti Médádì ń ṣe bíi wòlíì nínú ibùdó!” 28  Jóṣúà+ ọmọ Núnì tó jẹ́ ìránṣẹ́ Mósè láti kékeré fèsì pé: “Mósè olúwa mi, pa wọ́n lẹ́nu mọ́!”+ 29  Àmọ́ Mósè dá a lóhùn pé: “Ṣé ò ń jowú torí mi ni? Má ṣe bẹ́ẹ̀, ó wù mí kí gbogbo èèyàn Jèhófà jẹ́ wòlíì, kí Jèhófà sì fi ẹ̀mí rẹ̀ sára wọn!” 30  Lẹ́yìn náà, Mósè àti àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì pa dà sí ibùdó. 31  Jèhófà wá mú kí afẹ́fẹ́ kan fẹ́ wá lójijì, ó gbá àwọn ẹyẹ àparò wá láti òkun, ó sì mú kí wọ́n já bọ́ yí ibùdó+ náà ká, nǹkan bí ìrìn àjò ọjọ́ kan lápá ibí àti ìrìn àjò ọjọ́ kan lápá ọ̀hún, yí ibùdó náà ká, ìpele wọn sì ga tó nǹkan bí ìgbọ̀nwọ́* méjì sílẹ̀. 32  Tọ̀sántòru ọjọ́ yẹn àti gbogbo ọjọ́ kejì ni àwọn èèyàn náà ò fi sùn, tí wọ́n ń kó àparò. Kò sẹ́ni tó kó iye tó dín sí òṣùwọ̀n hómérì* mẹ́wàá, wọ́n sì ń sá a yí ibùdó náà ká. 33  Àmọ́ nígbà tí ẹran náà ṣì wà láàárín eyín wọn, kí wọ́n tó jẹ ẹ́ lẹ́nu, Jèhófà bínú sí àwọn èèyàn náà gidigidi, Jèhófà sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àwọn èèyàn náà lọ rẹpẹtẹ.+ 34  Wọ́n wá pe ibẹ̀ ní Kiburoti-hátááfà,*+ torí ibẹ̀ ni wọ́n sin àwọn èèyàn tó hùwà wọ̀bìà torí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ọkàn+ wọn sí. 35  Àwọn èèyàn náà kúrò ní Kiburoti-hátááfà lọ sí Hásérótì, wọ́n sì dúró sí Hásérótì.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ó túmọ̀ sí “Ó Ń Jó,” ìyẹn iná ajónirun; iná tó ń jó lala.
Ó jọ pé àwọn tí kì í ṣe ọmọ Ísírẹ́lì tó wà láàárín wọn ló ń sọ.
Tàbí “apálá.”
Tàbí “ọkàn wa.”
Tàbí “olùtọ́jú tó jẹ́ ọkùnrin.”
Tàbí “àwọn tí o mọ̀ sí.”
Ní Héb., “àwọn ọkùnrin tó ń fẹsẹ̀ rìn,” ìyẹn, àwọn ọkùnrin tó lè jagun.
Tàbí “wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í sọ tẹ́lẹ̀.”
Tàbí “àwọsánmà.”
Ìgbọ̀nwọ́ kan jẹ́ sẹ̀ǹtímítà 44.5 (ínǹṣì 17.5). Wo Àfikún B14.
Hómérì kan jẹ́ òṣùwọ̀n tó gba Lítà 220. Wo Àfikún B14.
Ó túmọ̀ sí “Ibi Ìsìnkú Àwọn Tó Ní Ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.”