Sáàmù 10:1-18

  • Jèhófà ni olùrànlọ́wọ́ àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́

    • Ẹni burúkú ń fọ́nnu pé: “Kò sí Ọlọ́run” (4)

    • Àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́ ń yíjú sọ́dọ̀ Jèhófà (14)

    • “Jèhófà ni Ọba títí láé” (16)

ל [Lámédì] 10  Jèhófà, kí nìdí tí o fi dúró lókèèrè? Kí nìdí tí o fi fara pa mọ́ ní àkókò wàhálà?+   Ẹni burúkú ń fi ìgbéraga lépa ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́,+Àmọ́ èrò ibi tó gbà máa yí dà lé e lórí.+   Ẹni burúkú ń fọ́nnu nítorí ìfẹ́ ọkàn ara rẹ̀,+Ó sì ń súre fún àwọn olójúkòkòrò;*נ [Núnì] Kì í bọ̀wọ̀ fún Jèhófà.   Ìgbéraga kì í jẹ́ kí ẹni burúkú ṣe ìwádìí kankan;Gbogbo èrò rẹ̀ ni pé: “Kò sí Ọlọ́run.”+   Àwọn ọ̀nà rẹ̀ ń yọrí sí rere,+Àmọ́ àwọn ìdájọ́ rẹ ga kọjá òye rẹ̀;+Ó ń fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ṣẹ̀sín.*   Ó ń sọ lọ́kàn rẹ̀ pé: “Mìmì kan ò ní mì mí;*Láti ìran dé ìran Mi ò ní rí àjálù láé.”+ פ [Péè]   Ègún, irọ́ àti ìhàlẹ̀ kún ẹnu rẹ̀;+Ìjàngbọ̀n àti jàǹbá wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.+   Ó ń lúgọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn ibùdó;Ó ń pa àwọn aláìṣẹ̀ láti ibi tó fara pa mọ́ sí.+ ע [Áyìn] Ojú rẹ̀ ń wá àwọn tó rin àrìnfẹsẹ̀sí.+   Ó ń dúró níbi tó fara pa mọ́ sí bíi kìnnìún nínú ihò rẹ̀.*+ Ó ń dúró láti mú ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́. Ó ń mú ẹni tí kò ní olùrànlọ́wọ́ nígbà tó bá pa àwọ̀n rẹ̀ dé.+ 10  Ẹni tó bá kó sí i lọ́wọ́ yóò di àtẹ̀rẹ́, yóò sì ṣubú lulẹ̀;Àwọn tó rin àrìnfẹsẹ̀sí yóò kó sínú akóló rẹ̀.* 11  Ó sọ lọ́kàn rẹ̀ pé: “Ọlọ́run ti gbàgbé.+ Ó ti gbé ojú rẹ̀ kúrò. Kò sì ní fiyè sí i láé.”+ ק [Kófì] 12  Jèhófà dìde.+ Ọlọ́run, gbé ọwọ́ rẹ sókè.+ Má gbàgbé àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.+ 13  Kí nìdí tí ẹni burúkú kò fi bọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run? Ó sọ lọ́kàn rẹ̀ pé: “O ò ní pè mí wá jíhìn.” ר [Réṣì] 14  Àmọ́, o rí ìjàngbọ̀n àti ìdààmú. Ò ń wò ó, o sì gbé ìgbésẹ̀.+ Ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn tó rin àrìnfẹsẹ̀sí yíjú sí;+Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ ọmọ aláìníbaba.*+ ש [Ṣínì] 15  Ṣẹ́ apá ẹni burúkú àti ẹni ibi,+Kó lè jẹ́ pé nígbà tí o bá wá ìwà burúkú rẹ̀,O ò ní rí i mọ́. 16  Jèhófà ni Ọba títí láé àti láéláé.+ Àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣègbé kúrò láyé.+ ת [Tọ́ọ̀] 17  Àmọ́ Jèhófà, wàá gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn oníwà pẹ̀lẹ́.+ Wàá mú ọkàn wọn dúró ṣinṣin,+ wàá sì fiyè sí wọn.+ 18  Wàá dá ẹjọ́ òdodo fún ọmọ aláìníbaba àti ẹni tí a ni lára,+Kí ẹni kíkú lásánlàsàn* má bàa dẹ́rù bà wọ́n mọ́.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí kó jẹ́, “Olójúkòkòrò ń súre fún ara rẹ̀.”
Tàbí “Ó ń wú fùkẹ̀ sí gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.”
Tàbí “Mi ò ní ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ (gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n).”
Tàbí “nínú igbó.”
Tàbí “àwọn èékánná rẹ̀ tó lágbára.”
Tàbí “aláìlóbìí.”
Ní Héb., “tó jẹ́ ará ayé.”