Sáàmù 51:1-19

  • Àdúrà ẹni tó ronú pìwà dà

    • Ẹlẹ́ṣẹ̀ látinú oyún wá (5)

    • “Wẹ̀ mí mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi” (7)

    • “Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi” (10)

    • Ọkàn tó gbọgbẹ́ wu Ọlọ́run (17)

Sí olùdarí. Orin Dáfídì, nígbà tíwòlíì Nátánì wọlé wá bá a lẹ́yìn tí Dáfídì bá Bátí-ṣébà lò pọ̀.+ 51  Ọlọ́run, ṣojú rere sí mi, nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀.+ Nu àwọn àṣìṣe mi kúrò nítorí ọ̀pọ̀ àánú rẹ.+   Wẹ̀ mí mọ́ tónítóní kúrò nínú ìṣìnà mi,+Kí o sì wẹ̀ mí mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.+   Nítorí mo mọ àwọn àṣìṣe mi dáadáa,Ẹ̀ṣẹ̀ mi sì wà níwájú mi* nígbà gbogbo.+   Ìwọ gan-an* ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí,+Mo ti ṣe ohun tó burú ní ojú rẹ.+ Torí náà, olódodo ni ọ́ nígbà tí o bá ń sọ̀rọ̀,Ìdájọ́ rẹ sì tọ́.+   Wò ó! A bí mi ní ẹlẹ́ṣẹ̀,Inú ẹ̀ṣẹ̀ sì ni ìyá mi* lóyún mi.+   Wò ó! Inú rẹ máa ń dùn sí òtítọ́ tó ti ọ̀kan ẹni wá;+Kọ́ inú mi lọ́hùn-ún* ní ọgbọ́n tòótọ́.   Fi hísópù wẹ̀ mí mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi, kí n lè mọ́;+Wẹ̀ mí, kí n lè funfun ju yìnyín lọ.+   Jẹ́ kí n gbọ́ ìró ayọ̀ àti ti ìdùnnú,Kí àwọn egungun mi tí ìwọ ti fọ́ lè máa yọ̀.+   Gbé ojú rẹ* kúrò lára àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mi,+Kí o sì pa gbogbo ìṣìnà mi rẹ́.*+ 10  Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,+Kí o sì fi ẹ̀mí tuntun sí inú mi,+ èyí tó fìdí múlẹ̀. 11  Má ṣe gbé mi sọ nù kúrò níwájú rẹ;Má sì gba ẹ̀mí mímọ́ rẹ kúrò lára mi. 12  Dá ayọ̀ ìgbàlà rẹ pa dà fún mi;+Kí o sì jẹ́ kó máa wù mí láti ṣègbọràn sí ọ.* 13  Màá kọ́ àwọn arúfin ní àwọn ọ̀nà rẹ,+Kí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ lè pa dà sọ́dọ̀ rẹ. 14  Gbà mí lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀,+ ìwọ Ọlọ́run, Ọlọ́run ìgbàlà mi,+Kí ahọ́n mi lè máa fi ìdùnnú kéde òdodo rẹ.+ 15  Jèhófà, ṣí ètè mi,Kí ẹnu mi lè máa kéde ìyìn rẹ.+ 16  Nítorí kì í ṣe ẹbọ ni ìwọ fẹ́, ká ní bẹ́ẹ̀ ni, mi ò bá ti rú u,+Kì í sì í ṣe odindi ẹbọ sísun ló ń mú inú rẹ dùn.+ 17  Àwọn ẹbọ tó ń mú inú Ọlọ́run dùn ni ọkàn tó gbọgbẹ́;Ìwọ Ọlọ́run, o kò ní pa ọkàn tó gbọgbẹ́ tó sì ní ìdààmú tì.*+ 18  Ṣe ohun rere fún Síónì nítorí inú rere rẹ;Mọ ògiri Jerúsálẹ́mù. 19  Nígbà náà, inú rẹ yóò máa dùn sí àwọn ẹbọ òdodo,Àwọn ẹbọ sísun àti àwọn odindi ẹbọ;A ó sì fi àwọn akọ màlúù rúbọ lórí pẹpẹ rẹ.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “lọ́kàn mi.”
Ní Héb., “Ìwọ nìkan.”
Tàbí “Ẹlẹ́ṣẹ̀ sì ni mí látìgbà tí ìyá mi ti.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “Pa ojú rẹ mọ́.”
Tàbí “nu gbogbo ìṣìnà mi kúrò.”
Ní Héb., “Kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìmúratán.”
Tàbí “fojú pa ọkàn tó gbọgbẹ́ tó sì ní ìdààmú rẹ́.”