Sáàmù 27:1-14
Ti Dáfídì.
27 Jèhófà ni ìmọ́lẹ̀ mi+ àti ìgbàlà mi.
Ta ni èmi yóò bẹ̀rù?+
Jèhófà ni odi ààbò ayé mi.+
Ta ni èmi yóò fòyà?
2 Nígbà tí àwọn ẹni ibi gbéjà kò mí láti jẹ ẹran ara mi,+Àwọn elénìní mi àti àwọn ọ̀tá mi ló kọsẹ̀ tí wọ́n sì ṣubú.
3 Bí àwọn ọmọ ogun tilẹ̀ pàgọ́ tì mí,Ọkàn mi kò ní bẹ̀rù.+
Bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi,Síbẹ̀, mi ò ní mikàn.
4 Ohun kan ni mo béèrè lọ́wọ́ Jèhófà,Òun ni mo sì ń wá, pé:
Kí n máa gbé inú ilé Jèhófà ní gbogbo ọjọ́ ayé mi,+Kí n máa rí adùn Jèhófà,Kí n sì máa fi ìmọrírì* wo tẹ́ńpìlì* rẹ̀.+
5 Nítorí yóò fi mí pa mọ́ sí ibi kọ́lọ́fín rẹ̀ ní ọjọ́ àjálù;+Yóò tọ́jú mi pa mọ́ sí ibi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀;+Yóò gbé mi sórí àpáta.+
6 Báyìí, orí mi yọ sókè ju àwọn ọ̀tá mi tó yí mi ká;Màá fi igbe ayọ̀ rú àwọn ẹbọ ní àgọ́ rẹ̀;Màá fi orin yin* Jèhófà.
7 Fetí sí mi, Jèhófà, nígbà tí mo bá ké pè ọ́;+Ṣojú rere sí mi, kí o sì dá mi lóhùn.+
8 Ọkàn mi gbẹnu sọ fún ọ, ó ní:
“Wá ọ̀nà láti rí ojú mi.”
Jèhófà, èmi yóò wá ọ̀nà láti rí ojú rẹ.+
9 Má fi ojú rẹ pa mọ́ fún mi.+
Má fi ìbínú lé ìránṣẹ́ rẹ kúrò.
Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi;+Má pa mí tì, má sì fi mí sílẹ̀, Ọlọ́run ìgbàlà mi.
10 Kódà, tí bàbá mi àti ìyá mi bá kọ̀ mí sílẹ̀,+Jèhófà fúnra rẹ̀ yóò tẹ́wọ́ gbà mí.+
11 Jèhófà, kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ,+Darí mi ní ọ̀nà ìdúróṣinṣin nítorí àwọn ọ̀tá mi.
12 Má fi mí lé ọwọ́ àwọn elénìní mi,*+Nítorí pé àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi,+Wọ́n sì ń halẹ̀ pé àwọn máa ṣe mí léṣe.
13 Ibo ni mi ò bá wà, ká ní mi ò ní ìgbàgbọ́Pé màá rí oore Jèhófà ní ilẹ̀ alààyè?*+
14 Gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà;+Ní ìgboyà, kí o sì mọ́kàn le.+
Bẹ́ẹ̀ ni, gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà.
Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
^ Tàbí “àròjinlẹ̀.”
^ Tàbí “ibi mímọ́.”
^ Tàbí “kọrin sí.”
^ Tàbí “Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àwọn elénìní mi ṣẹ lé mi lórí.”
^ Tàbí kó jẹ́, “Mo gbà gbọ́ dájú pé màá rí oore Jèhófà ní ilẹ̀ alààyè.”